Ifi 16
Àwọn Àwo tí Ó Kún fún Ibinu Ọlọrun
1 MO si gbọ́ ohùn nla kan lati inu tẹmpili wá, nwi fun awọn angẹli meje nì pe, Ẹ lọ, ẹ si tú ìgo ibinu Ọlọrun wọnni si ori ilẹ aiye. 2 Ekini si lọ, o si tú ìgo tirẹ̀ si ori ilẹ aiye; egbò kikẹ̀ ti o si dibajẹ si dá awọn enia ti o ni àmi ẹranko na, ati awọn ti nforibalẹ fun aworan rẹ̀. 3 Ekeji si tú ìgo tirẹ̀ sinu okun; o si dabi ẹ̀jẹ okú enia: gbogbo ọkàn alãye si kú ninu okun. 4 Ẹkẹta si tú ìgo tirẹ̀ sinu odò, ati si orisun awọn omi; nwọn si di ẹ̀jẹ. 5 Mo si gbọ́ angẹli ti omi nì wipe, Olododo ni Iwọ Ẹni-Mimọ́, ẹniti o mbẹ, ti o si ti wà, nitoriti iwọ ṣe idajọ bayi. 6 Nitoriti nwọn ti ta ẹ̀jẹ awọn enia mimọ́ ati ti awọn woli silẹ, iwọ si fi ẹ̀jẹ fun wọn mu; eyiyi li o yẹ wọn. 7 Mo si gbọ́ pẹpẹ nke wipe, Bẹ̃ni, Oluwa Ọlọrun Olodumare, otitọ ati ododo ni idajọ rẹ. 8 Ẹkẹrin si tú ìgo tirẹ̀ sori õrùn; a si yọnda fun u lati fi iná jó enia lara. 9 A si fi õru nla jo awọn enia lara, nwọn si sọ̀rọ-òdi si orukọ Ọlọrun, ẹniti o li agbara lori iyọnu wọnyi: nwọn kò si ronupiwada lati fi ogo fun u. 10 Ẹkarun si tu ìgo tirẹ̀ sori ìtẹ ẹranko na; ilẹ-ọba rẹ̀ si ṣokunkun; nwọn si nge ahọn wọn jẹ nitori irora. 11 Nwọn si sọ̀rọ-òdi si Ọlọrun ọrun nitori irora wọn ati nitori egbò wọn, nwọn kò si ronupiwada iṣẹ wọn. 12 Ẹkẹfa si tú ìgo tirẹ̀ sori odò nla Eufrate; omi rẹ̀ si gbẹ, ki a le pese ọna fun awọn ọba ati ìla-õrùn wá. 13 Mo si ri awọn ẹmí aimọ́ mẹta bi ọ̀pọlọ́, nwọn ti ẹnu dragoni na ati ẹnu ẹranko na ati ẹnu woli eke na jade wá. 14 Nitori ẹmi èṣu ni wọn, ti nṣe iṣẹ-iyanu, awọn ti njade lọ sọdọ awọn ọba gbogbo ilẹ aiye, lati gbá wọn jọ si ogun ọjọ nla Ọlọrun Olodumare. 15 Kiyesi i, mo mbọ̀ bi olè. Ibukún ni fun ẹniti nṣọna, ti o si npa aṣọ rẹ̀ mọ́, ki o má bã rìn ni ìhoho, nwọn a si ri itiju rẹ̀. 16 O si gbá wọn jọ si ibikan ti a npè ni Har-mageddoni li ède Heberu. 17 Ekeje si tú ìgo tirẹ̀ si oju ọrun; ohùn nla kan si ti inu tẹmpili jade lati ibi itẹ́, wipe, O pari. 18 Mànamána si kọ, a si gbọ́ ohùn, ãrá si san, ìṣẹlẹ nla si ṣẹ̀, iru eyiti kò ṣẹ̀ ri lati igbati enia ti wà lori ilẹ, iru ìṣẹlẹ nla bẹ̃, ti o si lagbara tobẹ̃. 19 Ilu nla na si pin si ipa mẹta, awọn orilẹ-ède si ṣubu: Babiloni nla si wá si iranti niwaju Ọlọrun, lati fi ãgo ọti-waini ti irunu ibinu rẹ̀ fun u. 20 Olukuluku erekuṣu si salọ, a kò si ri awọn òke nla mọ́. 21 Yinyín nla, ti ọkọ̃kan rẹ̀ to talenti ni ìwọ̀n, si bọ́ lù awọn enia lati ọrun wà: awọn enia si sọ̀rọ-òdi si Ọlọrun nitori iyọnu yinyín na; nitoriti iyọnu rẹ̀ na pọ̀ gidigidi.
Revelation 16
Six Bowls of Wrath
1 Then I heard a loud voice from the temple, saying to the seven angels, "Go and pour out on the earth the seven bowls of the wrath of God."
2 So the first angel went and poured out his bowl on the earth; and it became a loathsome and malignant sore on the people who had the mark of the beast and who worshiped his image.
3 The second angel poured out his bowl into the sea, and it became blood like that of a dead man; and every living tthing in the sea died.
4 Then the third angel poured out his bowl into the rivers and the springs of waters; and they became blood.5 And I heard the angel of the waters saying, "Righteous are You, who are and who were, O Holy One, because You judged these things;6 for they poured out the blood of saints and prophets, and You have given them blood to drink. They deserve it."7 And I heard the altar saying, "Yes, O Lord God, the Almighty, true and righteous are Your judgments."
8 The fourth angel poured out his bowl upon the sun, and it was given to it to scorch men with fire.9 Men were scorched with fierce heat; and they blasphemed the name of God who has the power over these plagues, and they did not repent so as to give Him glory.
10 Then the fifth angel poured out his bowl on the throne of the beast, and his kingdom became darkened; and they gnawed their tongues because of pain,11 and they blasphemed the God of heaven because of their pains and their sores; and they did not repent of their deeds.
12 The sixth angel poured out his bowl on the great river, the Euphrates; and its water was dried up, so that the way would be prepared for the kings from the east.
Armageddon
13 And I saw coming out of the mouth of the dragon and out of the mouth of the beast and out of the mouth of the false prophet, three unclean spirits like frogs;14 for they are spirits of demons, performing signs, which go out to the kings of the whole world, to gather them together for the war of the great day of God, the Almighty.15 ("Behold, I am coming like a thief. Blessed is the one who stays awake and keeps his clothes, so that he will not walk about naked and men will not see his shame.")16 And they gathered them together to the place which in Hebrew is called tHar-Magedon.
Seventh Bowl of Wrath
17 Then the seventh angel poured out his bowl upon the air, and a loud voice came out of the temple from the throne, saying, "It is done."18 And there were flashes of lightning and sounds and peals of thunder; and there was a great earthquake, such as there had not been since man came to be upon the earth, so great an earthquake was it, and so mighty.19 The great city was split into three parts, and the cities of the nations fell. Babylon the great was remembered before God, to give her the cup of the wine of His fierce wrath.20 And every island fled away, and the mountains were not found.21 And huge hailstones, about tone hundred pounds each, *came down from heaven upon men; and men blasphemed God because of the plague of the hail, because its plague *was extremely severe.