Sef 2
Ìpè sí Ìrònúpìwàdà
1 Ẹ kó ara nyin jọ pọ̀, ani, ẹ kójọ pọ̀ orilẹ-ède ti kò nani; 2 Ki a to pa aṣẹ na, ki ọjọ na to kọja bi iyàngbò, ki gbigboná ibinu Oluwa to de ba nyin, ki ọjọ ibinu Oluwa ki o to de ba nyin.
3 Ẹ wá Oluwa, gbogbo ẹnyin ọlọkàn tutù aiye, ti nṣe idajọ rẹ̀; ẹ wá ododo, ẹ wá ìwa-pẹ̀lẹ: boya a o pa nyin mọ li ọjọ ibinu Oluwa.Ìparun tí Yóo Dé Bá Àwọn Ìlú tí Wọ́n Yí Israẹli Ká
4 Nitoripe a o kọ̀ Gasa silẹ, Aṣkeloni yio si dahoro: nwọn o le Aṣdodu jade li ọsangangan, a o si fà Ekronu tu kuro. 5 Egbe ni fun awọn ẹniti ngbe agbègbe okun, orilẹ-ède awọn ara Kereti! ọ̀rọ Oluwa dojukọ nyin; iwọ Kenaani, ilẹ awọn ara Filistia, emi o tilẹ pa ọ run, ti ẹnikan kì yio gbe ibẹ̀ mọ. 6 Agbègbe okun yio si jẹ ibujoko ati agọ fun awọn olùṣọ agùtan, ati agbo fun agbo-ẹran. 7 Agbègbe na yio si wà fun iyokù ile Juda; nwọn o jẹ̀ li ori wọn: ni ile Aṣkeloni wọnni ni nwọn o dùbulẹ li aṣãlẹ: nitori Oluwa Ọlọrun wọn yio bẹ̀ wọn wò, yio si yi igbèkun wọn padà kuro. 8 Emi ti gbọ́ ẹgàn Moabu, ati ẹlẹyà awọn ọmọ Ammoni, nipa eyiti nwọn ti kẹgàn awọn enia mi, ti nwọn si ti gbe ara wọn ga si agbègbe wọn. 9 Nitorina bi emi ti wà, li Oluwa awọn ọmọ-ogun wi, Ọlọrun Israeli, Dajudaju Moabu yio dabi Sodomu, ati awọn ọmọ Ammoni bi Gomorra, bi titàn wèrepe, ati bi ihò iyọ, ati ìdahoro titi lai, iyokù awọn enia mi o kó wọn, iyokù awọn orilẹ-ède mi yio si jogun wọn. 10 Eyi ni nwọn o ni nitori igberaga wọn, nitoripe nwọn ti kẹgàn, nwọn si ti gbe ara wọn ga si enia Oluwa awọn ọmọ-ogun. 11 Oluwa yio jẹ ibẹ̀ru fun wọn: nitori on o mu ki gbogbo òriṣa ilẹ aiye ki o rù; enia yio si ma sìn i, olukuluku lati ipò rẹ̀ wá, ani gbogbo erekùṣu awọn keferi. 12 Ẹnyin ara Etiopia pẹlu, a o fi idà mi pa nyin. 13 On o si nà ọwọ́ rẹ̀ si ihà ariwa, yio si pa Assiria run; yio si sọ Ninefe di ahoro, ati di gbigbẹ bi aginjù. 14 Agbo-ẹran yio si dùbulẹ li ãrin rẹ̀, gbogbo ẹranko awọn orilẹ-ède: ati ẹiyẹ òfu ati õrẹ̀ yio ma gbe atẹrigbà rẹ̀, ohùn wọn yio kọrin li oju fèrese; idahoro yio wà ninu iloro: nitoriti on o ṣi iṣẹ kedari silẹ. 15 Eyi ni ilu alayọ̀ na ti o ti joko lainani ti o wi li ọkàn rẹ̀ pe, Emi ni, kò si si ẹnikan ti mbẹ lẹhìn mi: on ha ti ṣe di ahoro bayi, ibùgbe fun ẹranko lati dubulẹ si! olukuluku ẹniti o ba kọja lọdọ rẹ̀ yio pòṣe yio si mì ọwọ́ rẹ̀.
Zephaniah 2
Judgments on Judah's Enemies
1 Gather yourselves together, yes, gather,
O nation without shame,
2 Before the decree takes effect-
The day passes like the chaff-
Before the burning anger of the LORD comes upon you,
Before the day of the LORD'S anger comes upon you.
3 Seek the LORD,
All you humble of the earth
Who have carried out His ordinances;
Seek righteousness, seek humility.
Perhaps you will be hidden
In the day of the LORD'S anger.
4 For Gaza will be abandoned
And Ashkelon a desolation;
Ashdod will be driven out at noon
And Ekron will be uprooted.
5 Woe to the inhabitants of the seacoast,
The nation of the tCherethites!
The word of the LORD is against you,
O Canaan, land of the Philistines;
And I will destroy you
So that there will be no inhabitant.
6 So the seacoast will be pastures,
With caves for shepherds and folds for flocks.
7 And the coast will be
For the remnant of the house of Judah,
They will pasture on it.
In the houses of Ashkelon they will lie down at evening;
For the LORD their God will care for them
And restore their fortune.
8 "I have heard the taunting of Moab
And the revilings of the sons of Ammon,
With which they have taunted My people
And become arrogant against their territory.
9 "Therefore, as I live," declares the LORD of hosts,
The God of Israel,
"Surely Moab will be like Sodom
And the sons of Ammon like Gomorrah-
A place possessed by nettles and salt pits,
And a perpetual desolation.
The remnant of My people will plunder them
And the remainder of My nation will inherit them."10 This they will have in return for their pride, because they have taunted and become arrogant against the people of the LORD of hosts.11 The LORD will be terrifying to them, for He will starve all the gods of the earth; and all the coastlands of the nations will bow down to Him, everyone from his own place.
12 "You also, O Ethiopians, will be slain by My sword."
13 And He will stretch out His hand against the north
And destroy Assyria,
And He will make Nineveh a desolation,
Parched like the wilderness.
14 Flocks will lie down in her midst,
All beasts which range in herds;
Both the pelican and the hedgehog
Will lodge in the tops of her pillars;
Birds will sing in the window,
Desolation will be on the threshold;
For He has laid bare the cedar work.
15 This is the exultant city
Which dwells securely,
Who says in her heart,
"I am, and there is no one besides me."
How she has become a desolation,
A resting place for beasts!
Everyone who passes by her will hiss
And wave his hand in contempt.